Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 106:1-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Yin Olúwa Ẹ fi ìyìn fún Olúwa, nítorí tí o ṣeun.Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí tí ó ṣeun;Nítorí tí ìfẹ́ Rẹ̀ dúró láéláé.

2. Ta ni ó le ròyìn iṣẹ́ agbára Olúwata ni lè sọ nípa ìyìn Rẹ̀?

3. Ìbùkún ni fún àwọn tí ń pa ìdájọ́ mọ́?Ẹni tí tí ń ṣe ohun tí ó tọ́

4. Rántí mi, Olúwa,Nígbà tí ó bá fi ojú rere Rẹ̀ hàn,wá sí ìhà mi nígbà tí ìwọ bá gbà wọ́n,

5. Kí èmi kí ó lè jẹ ìgbádùn àlàáfíà àwọn tí ìwọ ti yànkí èmi kí ó sì darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyànìní Rẹ láti jọ yìn ọ́ lógo.

6. Àwa ti dẹ́sẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti ṣeàwa ti ṣe ohun tí kò dá aa sì ti hùwà búburú

7. Nígbà tí àwọn baba wa wà ní Éjíbítìiṣẹ́ ìyanu Rẹ kò yé wọnwọn kò rántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú Rẹgẹ́gẹ́ bí wọn ṣe sọ̀tẹ̀ sí ọ níbi òkun, àní nibi òkun pupa

Ka pipe ipin Sáàmù 106