26. Ó rán Mósè ìránṣẹ́ Rẹ̀àti Árónì tí ó ti yàn
27. Wọn ń ṣé iṣẹ́ ìyanu láàrin wọnó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Ámù
28. Ó rán òkùnkùn o sì mú ilẹ̀ ṣúwọn kò sì sọ̀rọ̀ òdì sí ọ̀rọ̀ Rẹ̀?
29. Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀,ó pa ẹja wọn.
30. Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá,èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
31. Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣnṣin sì dìde,ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
32. Ó sọ òjò di yìnyín,àti ọ̀wọ́ iná ní ilẹ̀ wọn;
33. Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọnó sì dá igi orílẹ̀ èdè wọn.
34. Ó sọ̀rọ̀, eésú sì dé,àti kòkòrò ní àìníye,
35. Wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn,wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run
36. Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn,ààyò gbogbo ipá wọ́n.
37. Ó mú Ísírẹ́lì jádeti òun ti fàdákà àti wúrà,nínú ẹ̀yà Rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
38. Inú Éjíbítì dùn nígbà tí wọn ń lọ,nítorí ẹ̀rù àwọn Ísírẹ́lí ń bá wọ́n.
39. Ó ta awọsánmọ̀ fún ìbòrí,àti iná láti fún wọn ni ìmọ́lẹ̀ lálẹ́