Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 104:29-35 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

29. Nígbà tí ìwọ bá pa ojú Rẹ mọ́ara kò rọ̀ wọ́nnígbà tí ìwọ bá mú ẹ̀mí wọn lọ,wọn ó kú, wọn o sì padà sí erùpẹ̀.

30. Nígbà tí ìwọ rán ẹ̀mí Rẹ,ní a dá wọn,ìwọ sì tún ojú ayé ṣe.

31. Jẹ́ kí ògo Olúwa wà pẹ́ títí láé;kí inú Olúwa kí ó dùn ní ti iṣẹ́ Rẹ̀

32. Ẹni tí ó wo ayé, tí ó sì wárìrì,ẹni tí ó fọwọ́ tọ́ àwọn òkè, tí wọ́n yọ èéfín.

33. Ní gbogbo ayé mí ní ń ó kọrin sí Olúwa:èmi ó kọrin ìyìn sí Olúwaníwọ̀n ìgbà tí mo wà láàyè.

34. Jẹ́ kí ẹ̀kọ́ mi kí ó tẹ ọ lọ́rùnbí mo tí ń yọ̀ nínú Olúwa.

35. Ṣùgbọ́n kí ẹlẹ́sẹ̀ kúrò láyékí ènìyàn búburú má sì sí mọ́.Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi.Yin Olúwa.

Ka pipe ipin Sáàmù 104