Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 104:18-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. Àwọn òkè gíga ni ààbò fún àwọn ewúrẹ́ igbó;àti àwọn àlàpà jẹ ààbò fún àwọn ehoro.

19. Òsúpá jẹ àmì fún àkókòòòrùn sì mọ̀ ìgbà tí yóò wọ̀.

20. Ìwọ mú òkùnkùn wá, ó sì di òru,nínú èyí tí gbogbo ẹ̀ranko igbó ń rìn kiri.

21. Kìnnìún ń bú ramúramù fún ohun ọdẹ wọnwọ́n sì ń wá oúnjẹ wọn láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.

22. Òòrùn ràn, wọn sì kó ara wọn jọ,wọn padà lọ dùbúlẹ̀ sí ìhò wọn.

23. Ọkùnrin jáde lọ sí iṣẹ́ wọn,àti sí làálàá Rẹ̀ títí di àṣálẹ́.

24. Iṣẹ́ Rẹ ti pọ̀ tó, Olúwa!Nínú ọgbọ́n ni ìwọ ṣe gbogbo wọn:ayé kún fún àwọn ìṣẹ̀dá a Rẹ.

Ka pipe ipin Sáàmù 104