Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 102:8-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Ní ọjọ́ gbogbo àwọn ọ̀ta ológosẹ́ mi ń gàn mí;àwọn tí ń ṣe ìkanra sí mi ń fi orúkọ mi bú.

9. Èmi jẹ eérú gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ mi, èmi si da ohun mímu mi pọ̀ pẹ̀lú omíjé.

10. Nítorí ìbínú ríru Rẹ, nítorí ìwọ ti gbé mi sókè, ìwọ sì gbé mi ṣánlẹ̀.

11. Ọjọ́ mi dàbí òjìji àṣálẹ́èmi sì rọ bí koríko

12. Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, ni yóò dúró láéláé;ìrántí Rẹ láti ìran dé ìran.

13. Ìwọ ó dìde ìwọ o sì ṣàánú fún Síónì,nítorí ìgbà àti ṣe ojú rere sí i;àkókò náà ti dé.

14. Nítorí tí àwọn òkúta jẹ́ inú dídùnsí àwọn ìránṣẹ́ Rẹ; wọ́n sì káànú ẹrùpẹ̀ Rẹ.

15. Àwọn ayé yóò bẹ̀rù orúkọ Olúwa,gbogbo ọba ayé yóò máa bẹ̀rù ògo Rẹ.

Ka pipe ipin Sáàmù 102