Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 102:17-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Yóò dáhùn àdúrà àwọn aláìní;kì yóò si gan ẹ̀bẹ̀ wọn.

18. Jẹ́ kí a kọ èyí fún ìran tí ń bọ̀,àwọn ènìyàn tí a kò tí ì dá yóò yin Olúwa:

19. “Olúwa wo ilẹ̀ láti òkè mímọ́ Rẹ̀ wáláti ọ̀run wá ni ó bojúwo ayé,

20. Láti gbọ́ ìrora ará túbú, lati túàwọn tí a yàn sí ikú sílẹ̀.”

21. Kí a lè sọ orúkọ Olúwa ni Síónìàti ìyìn Rẹ̀ ní Jérúsálẹ́mù.

22. Ní ìgbà tí a kó àwọn ènìyàn àtiìjọba pọ̀ láti máa sìn Olúwa.

23. Ní ipa ọ̀nà mi, ó Rẹ agbára mi sílẹ̀,ó gé ọjọ́ mi kúrú.

24. Èmi sì wí pé;“Ọlọ́run mi, Má ṣe mú mi kúrò ní agbede-méjì ọjọ́ mi; ọdún Rẹ̀ ń lọ láti ìran dé ìran.

25. Ní ìbẹ̀rẹ̀ ní ìwọ fi ìpilẹ̀ ayé sọlẹ̀,ọrun si jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ Rẹ.

26. Wọn yóò ṣègbé, wọn yóò parun, ṣùgbọ́n ìwọ yóò wà;gbogbo wọn ni yóò gbó bí aṣọ.Bí ẹ̀wù ni ìwọ yóò pààrọ̀ wọnwọn yóò sì di àpatì.

Ka pipe ipin Sáàmù 102