Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 10:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Èé ha ti ṣe, Olúwa, tí ìwọ fi dúró ní òkè réré?È ha ti ṣe tí ìwọ fi ara Rẹ pamọ́ ní ìgbà ìpọ́njú?

2. Nínú àrékérekè ènìyàn búburú ti ó gbérò ni kí a ti mú wọn,lí a mú-un nínú ìlànà tí o gbérò.

3. Ó ń fọ́nnu nínú ìfẹ́ inú ọkàn Rẹ̀;o bùkún olójúkòkòrò ó sì ń kẹ́gàn Olúwa

4. Ènìyàn búburú kò lè rí i nínú ìgbéraga Rẹ̀;kò sí àyè fún Ọlọ́run nínú gbogbo èrò Rẹ̀;

5. Ọ̀nà Rẹ̀ ń gún régé nígbà gbogbo;òun ń gbéraga, òfin Rẹ sì jìnnà sí i;òun kẹ́gàn àwọn ọ̀ta Rẹ̀.

6. O wí fún ara Rẹ̀, “Kò si ohun tí ó le mì mí;Inú mi yóò máa dùn nígbà gbogbo èmi kò si ní ní wàhálà.”

Ka pipe ipin Sáàmù 10