Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 10:1-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Èé ha ti ṣe, Olúwa, tí ìwọ fi dúró ní òkè réré?È ha ti ṣe tí ìwọ fi ara Rẹ pamọ́ ní ìgbà ìpọ́njú?

2. Nínú àrékérekè ènìyàn búburú ti ó gbérò ni kí a ti mú wọn,lí a mú-un nínú ìlànà tí o gbérò.

3. Ó ń fọ́nnu nínú ìfẹ́ inú ọkàn Rẹ̀;o bùkún olójúkòkòrò ó sì ń kẹ́gàn Olúwa

4. Ènìyàn búburú kò lè rí i nínú ìgbéraga Rẹ̀;kò sí àyè fún Ọlọ́run nínú gbogbo èrò Rẹ̀;

5. Ọ̀nà Rẹ̀ ń gún régé nígbà gbogbo;òun ń gbéraga, òfin Rẹ sì jìnnà sí i;òun kẹ́gàn àwọn ọ̀ta Rẹ̀.

6. O wí fún ara Rẹ̀, “Kò si ohun tí ó le mì mí;Inú mi yóò máa dùn nígbà gbogbo èmi kò si ní ní wàhálà.”

7. Ẹnu Rẹ̀ kún fún ẹ̀gàn àti irọ́ àti ìtànjẹ;wàhálà àti ohun búburú wa lábẹ́ ahọ́n Rẹ̀.

8. Ó lúgọ ní bùba nítòsí ìletò;ó gọ níbi ìkọ̀kọ̀ láti pa aláìṣẹ̀,ojú Rẹ̀ ń ṣọ́ àwọn talákà ní ìkọ̀kọ̀.

9. O lúgọ ní bùba nínú pàǹtí;ó lúgọ ní bùba làti mú àwọn aláìní ìrànwọ́;ó mú àwọn aláìlólùrànlọ́wọ́, ó sì wọ́ wọn lọ sínú àwọ̀n Rẹ̀.

10. Àwọn ẹni ìpalára Rẹ̀ run, ó Rẹ ara Rẹ̀ sílẹ̀;kí talákà bá a le bọ́ sí ọwọ́ agbára Rẹ̀.

11. Ó wí fún ara Rẹ̀, “Ọlọ́run ti gbàgbé;Ó pa ojú Rẹ̀ mọ́ òun kì yóò rí i láéláé.”

12. Dìde, Olúwa! Gbé ọwọ́ Rẹ̀ sókè, Ọlọ́run.Má ṣe gbàgbé àwọn olùpọ́njú.

13. Èeṣe tí ènìyàn búburú ṣe ń kẹ́gàn Ọlọ́run?Èéṣe tí o fi wí nínú ọkàn ara Rẹ̀,“Kò ní pé mí láti ṣe ìṣirò”?

14. Ṣùgbọ́n ìwọ, Ọlọ́run, ni o ri wàhálà àti ìrora;Ìwọ rò láti fi sí ọwọ́ Rẹ.talákà fara Rẹ̀ jin fún ọ;Ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ àwọn aláìní baba.

15. Ṣẹ́ apá àwọn ènìyàn búburú àti ènìyàn ibi;pèé láti wa sírò fún iwà ìkà Rẹ̀tí a kò le è rí.

Ka pipe ipin Sáàmù 10