Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 9:8-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Má ṣe bá ẹlẹ́gàn wí, àìṣebẹ́ẹ̀ yóò kórìíra rẹ.Bá Ọlọgbọ́n wí yóò sì fẹ́ràn rẹ;

9. kọ́ Ọlọgbọ́n ènìyàn lẹ́kọ̀ọ́, yóò sì gbọ́n sí ikọ́ Olódodo ènìyàn lẹ́kọ̀ọ́, yóò sì fi kún ìmọ̀ rẹ̀.

10. “Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìbẹ̀rẹ̀ ọgbọ́n,ìmọ̀ nípa Ẹni mímọ́ ni òye.

11. Nítorí nípasẹ̀ mi ọjọ́ rẹ yóò gùnọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún yóò sì kún ọjọ́ ayé rẹ.

12. Bí ìwọ bá gbọ́n, ọgbọ́n rẹ yóò fún ọ ní èrè:bí ìwọ bá jẹ́ ẹlẹ́gàn, ìwọ nìkan ni yóò jìyà.”

13. Òmùgọ̀ obìnrin jẹ́ aláriwo;ó jẹ́ aláìlẹ́kọ̀ọ́ àti aláì ní ìmọ̀.

14. Ó jókòó lẹ́nu ọ̀nà ilé rẹ̀lórí ìjòkó níbi tí ó ga jù láàrin ìlú,

15. ó ń pe àwọn tí ó ń kọjá lọ,tí wọn ń lọ tààrà ní ọ̀nà wọn.

16. “Jẹ́ kí gbogbo ẹni tí ó jẹ́ aláìlóye súnmọ́ bí!”Ni ó wí fún ẹni tí òye kù díẹ̀ ká à tó fún.

17. “Omi tí a jí mu dùnoúnjẹ tí a jẹ ní ìkọ̀kọ̀ a máa ládùn!”

18. Ṣùgbọ́n wọn ò funra pé àwọn òkú wà níbẹ̀,pé àwọn àlejò rẹ̀ wà ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀ isà òkú.

Ka pipe ipin Òwe 9