Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 9:1-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ọgbọ́n ti kọ́ ilé rẹ̀,ó ti gbẹ́ òpó o rẹ̀ méjèèjì

2. ó ti fi ilé pọn tí ó ti fọ̀nà rokàó sì ti ṣètò o tábìlì oúnjẹ rẹ̀

3. ó ti rán àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ jáde, ó sì ń pè,láti ibi tí ó ga jù láàrin ìlú.

4. “Jẹ́ kí gbogbo àwọn aláìgbọ́n wọ ibí wá!”Ó ń wí fún àwọn tí kò lọ́gbọ́n pé

5. “Wá, ẹ wá fẹ́ oúnjẹ misì mu wáìnì tí mo ti pò pọ̀.

6. Fi ìwà àìmọ̀kan rẹ sílẹ̀ ìwọ yóò sì yè;rìn ní ọ̀nà òye.

7. “Ẹnikẹ́ni tí ó bá bá ẹlẹ́gàn wí, kọ lẹ́tà sí àbùkùẹnikẹ́ni tí ó bá bá ẹni búburú wí kọ lẹ́tà sí èébú.

8. Má ṣe bá ẹlẹ́gàn wí, àìṣebẹ́ẹ̀ yóò kórìíra rẹ.Bá Ọlọgbọ́n wí yóò sì fẹ́ràn rẹ;

9. kọ́ Ọlọgbọ́n ènìyàn lẹ́kọ̀ọ́, yóò sì gbọ́n sí ikọ́ Olódodo ènìyàn lẹ́kọ̀ọ́, yóò sì fi kún ìmọ̀ rẹ̀.

Ka pipe ipin Òwe 9