Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 9:1-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ọgbọ́n ti kọ́ ilé rẹ̀,ó ti gbẹ́ òpó o rẹ̀ méjèèjì

2. ó ti fi ilé pọn tí ó ti fọ̀nà rokàó sì ti ṣètò o tábìlì oúnjẹ rẹ̀

3. ó ti rán àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ jáde, ó sì ń pè,láti ibi tí ó ga jù láàrin ìlú.

4. “Jẹ́ kí gbogbo àwọn aláìgbọ́n wọ ibí wá!”Ó ń wí fún àwọn tí kò lọ́gbọ́n pé

5. “Wá, ẹ wá fẹ́ oúnjẹ misì mu wáìnì tí mo ti pò pọ̀.

6. Fi ìwà àìmọ̀kan rẹ sílẹ̀ ìwọ yóò sì yè;rìn ní ọ̀nà òye.

7. “Ẹnikẹ́ni tí ó bá bá ẹlẹ́gàn wí, kọ lẹ́tà sí àbùkùẹnikẹ́ni tí ó bá bá ẹni búburú wí kọ lẹ́tà sí èébú.

8. Má ṣe bá ẹlẹ́gàn wí, àìṣebẹ́ẹ̀ yóò kórìíra rẹ.Bá Ọlọgbọ́n wí yóò sì fẹ́ràn rẹ;

9. kọ́ Ọlọgbọ́n ènìyàn lẹ́kọ̀ọ́, yóò sì gbọ́n sí ikọ́ Olódodo ènìyàn lẹ́kọ̀ọ́, yóò sì fi kún ìmọ̀ rẹ̀.

10. “Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìbẹ̀rẹ̀ ọgbọ́n,ìmọ̀ nípa Ẹni mímọ́ ni òye.

11. Nítorí nípasẹ̀ mi ọjọ́ rẹ yóò gùnọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún yóò sì kún ọjọ́ ayé rẹ.

12. Bí ìwọ bá gbọ́n, ọgbọ́n rẹ yóò fún ọ ní èrè:bí ìwọ bá jẹ́ ẹlẹ́gàn, ìwọ nìkan ni yóò jìyà.”

13. Òmùgọ̀ obìnrin jẹ́ aláriwo;ó jẹ́ aláìlẹ́kọ̀ọ́ àti aláì ní ìmọ̀.

14. Ó jókòó lẹ́nu ọ̀nà ilé rẹ̀lórí ìjòkó níbi tí ó ga jù láàrin ìlú,

Ka pipe ipin Òwe 9