Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 6:7-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Kò ní olùdarí,kò sí alábojútó tàbí ọba,

8. síbẹ̀, a kó ìpèsè rẹ̀ jọ ní àsìkò òjòyóò sì kó oúnjẹ rẹ̀ jọ ní àsìkò ìkórè.

9. Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò dùbúlẹ̀, ìwọ ọ̀lẹ?Nígbà wo ni ìwọ yóò jí kúrò lójú oorun rẹ?

10. Oorun díẹ̀, Òògbé díẹ̀,ìkáwọ́gbera láti sinmi díẹ̀

11. Òsì yóò sì wá sórí rẹ bí ìgárá ọlọ́ṣààti àìní bí adigunjalè.

12. Ènìyàn kénìyàn àti ènìyàn búburú,tí ń ru ẹnu àrékérekè káàkiri,

13. tí ó ń sẹ́jú pàkòpàkò,ó ń fi ẹsẹ̀ ṣe àmìó sì ń fi ìka ọwọ́ rẹ̀ júwe,

14. tí ó ń pète búburú pẹ̀lú ẹ̀tàn nínú ọkàn rẹ̀ìgbà gbogbo ni ó máa ń dá ìjà sílẹ̀.

15. Nítorí náà ìdààmú yóò dé báa ní ìsẹ́jú akàn;yóò parun lójijì láì sí àtúnṣe.

Ka pipe ipin Òwe 6