Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 6:12-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Ènìyàn kénìyàn àti ènìyàn búburú,tí ń ru ẹnu àrékérekè káàkiri,

13. tí ó ń sẹ́jú pàkòpàkò,ó ń fi ẹsẹ̀ ṣe àmìó sì ń fi ìka ọwọ́ rẹ̀ júwe,

14. tí ó ń pète búburú pẹ̀lú ẹ̀tàn nínú ọkàn rẹ̀ìgbà gbogbo ni ó máa ń dá ìjà sílẹ̀.

15. Nítorí náà ìdààmú yóò dé báa ní ìsẹ́jú akàn;yóò parun lójijì láì sí àtúnṣe.

16. Àwọn ohun mẹ́fà wà tí Olúwa kórìíra,ohun méje ní ó jẹ́ ìríra síi:

17. Ojú ìgbéraga,Ahọ́n tó ń parọ́ọwọ́ tí ń ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀,

18. ọkàn tí ń pète ohun búburú,ẹsẹ̀ tí ó yára láti sáré sínú ìwà ìkà,

19. Ajẹ́rìí èké tí ń tú irọ́ jáde lẹ́nuàti ènìyàn tí ń dá ìjà sílẹ̀ láàrin àwọn ọmọ ìyá kan.

20. Ọmọ mi, pa àṣẹ baba rẹ mọ́má sì ṣe kọ ẹ̀kọ́ ìyá rẹ sílẹ̀.

21. Jẹ́ kí wọn wà nínú ọkàn rẹ láéláéso wọ́n mọ́ ọrùn rẹ

22. Nígbà tí ìwọ bá ń rìn, wọn yóò ṣe amọ̀nà rẹ;nígbà tí ìwọ bá sùn, wọn yóò máa ṣe olùsọ́ rẹ;nígbà tí o bá jí, wọn yóò bá ọ sọ̀rọ̀.

23. Nítorí àwọn àṣẹ yìí jẹ́ àtùpà,ẹ̀kọ́ yìí jẹ́ ìmọ́lẹ̀,àti ìtọ́niṣọ́nà ti ìbáwíni ọ̀nà sí ìyè

24. yóò pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́dọ̀ obìnrin oníṣekúṣekúrò lọ́wọ́ ẹnu dídùn aya tí ń rin ìrìnkurìn

Ka pipe ipin Òwe 6