Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 31:22-29 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

22. Ó ṣe aṣọ títẹ́ fún ibùsùn rẹ̀;ẹwu dáradára àti eléṣè é àlùkò ni aṣọ rẹ̀

23. A bọ̀wọ̀ fún ọkọ rẹ̀ ní ẹnu ibòde ìlúníbi tí ó ń jókòó láàrin àwọn àgbà ìlú

24. Ó ń ṣe àwọn aṣọ dáradára ó sì ń tà wọ́nó sì ń kó ọjà fún àwọn oníṣòwò

25. Agbára àti ọlá ni ó wò ọ́ láṣọó le fi ọjọ́ iwájú rẹ́rìn-ín.

26. A sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọgbọ́nìkọ́ni òtítọ́ sì ń bẹ létè e rẹ̀

27. Ó ń bojú tó gbogbo ètò ilé rẹ̀kì í sì í jẹ oúnjẹ ìmẹ́lẹ́

28. Àwọn ọmọ rẹ̀ dìde wọ́n sì pè é ní alábùkúnọkọ rẹ̀ pẹ̀lú ń gbóríyìn fún un

29. “Ọ̀pọ̀lọpọ̀ òbìnrin ní ń ṣe nǹkan ọlọ́láṣùgbọ́n ìwọ ju gbogbo wọn lọ”

Ka pipe ipin Òwe 31