Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 31:20-25 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

20. ó la ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn talákàó sì na ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn aláìní.

21. Nígbà tí òjò dídì rọ̀, kò bẹ̀rù nítorí ìdílé rẹ̀nítorí gbogbo wọn ni ó wọ aṣọ tí ó nípọn.

22. Ó ṣe aṣọ títẹ́ fún ibùsùn rẹ̀;ẹwu dáradára àti eléṣè é àlùkò ni aṣọ rẹ̀

23. A bọ̀wọ̀ fún ọkọ rẹ̀ ní ẹnu ibòde ìlúníbi tí ó ń jókòó láàrin àwọn àgbà ìlú

24. Ó ń ṣe àwọn aṣọ dáradára ó sì ń tà wọ́nó sì ń kó ọjà fún àwọn oníṣòwò

25. Agbára àti ọlá ni ó wò ọ́ láṣọó le fi ọjọ́ iwájú rẹ́rìn-ín.

Ka pipe ipin Òwe 31