Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 31:2-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. “Ìwọ ọmọ mi, ìwọ ọmọ inú mi,ìwọ ọmọ ẹ̀jẹ̀ mi.

3. Má ṣe lo agbára rẹ lórí obìnrin,okun rẹ lórí àwọn tí ó pa àwọn ọba run.

4. “Kì í ṣe fún àwọn ọba, ìwọ Lémúélìkì í ṣe fún ọba láti mu ọtí wáìnìkì í ṣe fún alákòóso láti máa wá ọtí líle

5. Kí wọn má ba à mu ọtí yó kí wọn sì gbàgbé ohun tí òfin wíkí wọn sì fi ẹ̀tọ́ àwọn tí ara ń ni dù wọ́n

6. Fi ọtí líle fún àwọn tí ń ṣègbéwáìnì fún àwọn tí ó wà nínú ìrora;

7. Jẹ́ kí wọn mu ọtí kí wọn sì gbàgbé òsì wọnkí wọn má sì rántí òsì wọn mọ́.

8. “Ṣọ̀rọ̀ lórúkọ àwọn tí kò le sọ̀rọ̀ fún ra wọnfún ẹ̀tọ́ àwọn ẹni tí ń parun

9. sọ̀rọ̀ kí o sì ṣe ìdájọ́ àìṣègbèjà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà àti aláìní.”

10. Ta ni ó le rí aya oníwà rere?Ó níye lórí ju iyùn lọ

11. ọkọ rẹ̀ ní ìgbẹ́kẹ̀lẹ́ púpọ̀ nínú rẹ̀kò sì sí ìwà rere tí kò pé lọ́wọ́ rẹ̀.

12. Ire ní ó ń ṣe fún un, kì í ṣe ibiní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.

13. Ó sa aṣọ irun àgùtàn olówùú àti ọ̀gbọ̀Ó sì ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ìyárí.

Ka pipe ipin Òwe 31