Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 30:8-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Mú èké ṣíṣe àti irọ́ jìnnà sí mi;má ṣe fún mi ní òsì tàbí ọrọ̀,ṣùgbọ́n fún mi ní oúnjẹ òòjọ́ mi nìkan,

9. Àìṣe bẹ́ẹ̀, mo lè ní àníjù kí n sì gbàgbé rẹkí ń sì wí pé, ‘Ta ni Olúwa?’Tàbí kí ń di òtòsì kí ń sì jalèkí ń sì ṣe àìbọ̀wọ̀ fún orúkọ Ọlọ́run mi.

10. “Má ṣe ba ìránṣẹ́ lórúkọ jẹ́ lọ́dọ̀ ọ̀gá rẹ̀àìṣe bẹ́ẹ̀ yóò ṣẹ́ èpè lé ọ. Ìwọ yóò sì jìyà rẹ̀.

11. “Àwọn kan wá ṣépè fún àwọn baba wọntí wọn kò sì ṣúre fún àwọn ìyá wọn:

12. Àwọn tí ó mọ́ ní ojú ara wọnṣíbẹ̀ tí wọn kò sì mọ́ kúrò nínú èérí wọn;

13. Àwọn ẹni tí ojú wọn gbéga nígbà gbogbo,tí ìwolẹ̀ wọn sì kún fún ìgbéraga.

14. Àwọn ẹni tí eyín wọn jẹ́ idàÀwọn tí èrìgì wọn kún fún ọ̀bẹláti jẹ àwọn talákà run kúrò ní ilẹ̀ ayéàwọn aláìní kúrò láàrin àwọn ọmọ ènìyàn.

15. “Eṣúṣú ni ọmọbìnrin méjì‘Múwá! Múwá!’ ní wọn ń ké.“Àwọn nǹkan mẹ́ta kan wà tí kò ní ìtẹ́lọ́rùn láéláé,mẹ́rin tí kò jẹ́ wí láéláé pé, ‘Ó tó’:

16. Ibojì, inú tí ó yàgàn,ilẹ̀, tí omi kì í tẹ́lọ́rùn láéláé,àti iná, tí kì í wí láéláé pé, ‘Ó tó!’

17. “Ojú tí ń fi baba ṣẹ̀fẹ̀,tí ó kẹ́gàn ìgbọràn sí ìyáẹyẹ àkálá ẹ̀bá odò ni yóò yọ ọ́,igún yóò mú un jẹ.

18. “Àwọn nǹkan mẹ́ta wà tí ó jẹ́ ìyàlẹ́nu fún mi,mẹ́rin tí kò yé mi:

Ka pipe ipin Òwe 30