Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 30:19-32 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Ipa idì ní òfuurufúipa ejò lórí àpátaipa ọkọ̀ ojú omi lójú agbami òkunàti ipa ọ̀nà ọkùnrin tí ó mú wúndíá lọ́wọ́.

20. “Èyí ni ọ̀nà alágbérè obìnrinó jẹun o sì nu ẹnu rẹ̀ó sì wí pé, N kò ṣe ohunkóhun tí kò tọ́.

21. “Lábẹ́ nǹkan mẹ́ta ni ile ayé ti ń wárìrìlábẹ́ ohun mẹ́rin ni kò ti lè mí fín ín.

22. Ìránṣẹ́ tí ó di Ọbaaláìgbọ́n tí ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ oúnjẹ́

23. Obìnrin tí gbogbo ènìyàn kórìíra tí ó sì wá lọ́kọìránṣẹ́bìnrin tí ó gbọkọ mọ́ ọ̀gá rẹ̀ lọ́wọ́.

24. “Àwọn ohun mẹ́rin ló kéré láyésíbẹ̀ wọ́n gbọ́n gidigidi;

25. Àwọn èrà jẹ́ ẹ̀dá tí ó ní agbára díẹ̀síbẹ̀ wọ́n kó oúnjẹ wọn pamọ́ ní àsìkò òjò

26. Ehoro jẹ́ ẹ̀dá tí kò ní agbára púpọ̀ṣíbẹ̀ wọ́n ń ṣe ilé wọn sí ibi ihò àpáta;

27. Eṣú kò ní ọbaṣíbẹ̀ wọ́n ń jáde lọ papọ̀ ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́

28. a lè fi ọwọ́ mú aláǹgbáṣíbẹ̀ a ń rí i ní ààfin ọba.

29. “Àwọn ohun mẹ́ta ní n bẹ tí ń rìn rere,ohun mẹ́rin tí ń kọrí sí ibi rere,

30. Kìnnìún, alágbára láàrin ẹrankotí kì í sá fún ohunkóhun

31. Ẹsin tí a dì lẹ́gbẹ̀ẹ́; àti òbúkọ,àti ọba pẹ̀lú àwọn ọmọ ogun rẹ̀ láyìíká rẹ̀.

32. “Bí ìwọ bá ti hùwà aṣiwèrè nípa gbígbé ara rẹ ga,tàbí tí o bá ti gbèrò ibi,da ọwọ́ rẹ bo ẹnu rẹ!

Ka pipe ipin Òwe 30