Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 30:1-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Àwọn ọ̀rọ̀ Ágúrì ọmọ Jákè, ọ̀rọ̀ ìṣọtẹ́lẹ̀ tí ọkùnrin yìí sọ fún Ítíélì, sí Ítíélì àti sí Úkálì:

2. “Èmi ni aláìmòye ju nínú àwọn ènìyàn;N kò ní òye ènìyàn.

3. Èmi kò tilẹ̀ kọ́ ọgbọ́ntàbí ní ìmọ̀ ẹni mímọ́ nì

4. Ta ni ó ti gòkè lọ sí ọ̀run tí ó sì padà sọ̀kalẹ̀?Ta ni ó ti kó afẹ́fẹ́ jọ sí ihò àtẹ́lẹwọ́ rẹ̀?Ta ni ó ti ta kókó omi sétí aṣọ?Ta ni ó fi gbogbo ìpìlẹ̀ ayé lélẹ̀?Kí ni orúkọ rẹ̀, àti orúkọ ọmọ rẹ̀?Sọ fún mi bí o bá mọ̀.

5. “Gbogbo ọ̀rọ̀ Ọlọ́run jẹ́ aláìlábùkù;oun ni ààbò fún gbogbo ẹni fi í ṣe ibi ìpamọ́ wọn

6. Má ṣe fi kún ọ̀rọ̀ rẹ̀,àìṣe bẹ́ẹ̀ yóò bá ọ wí yóò sì sọ ọ́ di òpùrọ́.

7. “Ohun méjì ni mo ń bèèrè lọ́wọ́ rẹ, Olúwa;má ṣe fi wọ́n dù mí kí ń tó kú:

8. Mú èké ṣíṣe àti irọ́ jìnnà sí mi;má ṣe fún mi ní òsì tàbí ọrọ̀,ṣùgbọ́n fún mi ní oúnjẹ òòjọ́ mi nìkan,

9. Àìṣe bẹ́ẹ̀, mo lè ní àníjù kí n sì gbàgbé rẹkí ń sì wí pé, ‘Ta ni Olúwa?’Tàbí kí ń di òtòsì kí ń sì jalèkí ń sì ṣe àìbọ̀wọ̀ fún orúkọ Ọlọ́run mi.

10. “Má ṣe ba ìránṣẹ́ lórúkọ jẹ́ lọ́dọ̀ ọ̀gá rẹ̀àìṣe bẹ́ẹ̀ yóò ṣẹ́ èpè lé ọ. Ìwọ yóò sì jìyà rẹ̀.

11. “Àwọn kan wá ṣépè fún àwọn baba wọntí wọn kò sì ṣúre fún àwọn ìyá wọn:

12. Àwọn tí ó mọ́ ní ojú ara wọnṣíbẹ̀ tí wọn kò sì mọ́ kúrò nínú èérí wọn;

13. Àwọn ẹni tí ojú wọn gbéga nígbà gbogbo,tí ìwolẹ̀ wọn sì kún fún ìgbéraga.

14. Àwọn ẹni tí eyín wọn jẹ́ idàÀwọn tí èrìgì wọn kún fún ọ̀bẹláti jẹ àwọn talákà run kúrò ní ilẹ̀ ayéàwọn aláìní kúrò láàrin àwọn ọmọ ènìyàn.

Ka pipe ipin Òwe 30