4. Nígbà náà ni ìwọ yóò rí ojú rere àti orúkọ rerení ojú Ọlọ́run àti lójú ènìyàn.
5. Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹmá ṣe sinmi lé òye ara à rẹ;
6. Jẹ́wọ́ rẹ̀ ní gbogbo ọ̀nà rẹyóò sì ṣe àkóso ọ̀nà rẹ.
7. Má ṣe jẹ́ ọlọ́gbọ́n lójú ara à rẹbẹ̀rù Olúwa kí o sì kórìíra ibi.
8. Èyí yóò mú ìlera fún ara à rẹàti okun fún àwọn egungun rẹ.
9. Fi ọrọ̀ rẹ bọ̀wọ̀ fún Olúwa,pẹ̀lú àkọ́so oko ò rẹ
10. Nígbà náà ni àká rẹ yóò kún àkúnyaàgbá rẹ yóò kún à kún wọ́ sílẹ̀ fún wáìnì tuntun.
11. Ọmọ mi, má ṣe kẹ́gàn ìbáwí Olúwamá si ṣe bínú nígbà tí ó bá ń bá ọ wí,
12. Nítorí Olúwa a máa bá àwọn tí ó fẹ́ràn wíbí baba ti í bá ọmọ tí ó bá nínú dídùn sí wí.
13. Ìbùkún ni fún ẹni tí ó ní ìmọ̀,ẹni tí ó tún ní òye síi
14. Nítorí ó ṣe èrè ju fàdákà lọó sì ní èrè lórí ju wúrà lọ.
15. Ó ṣe iyebíye ju iyùn lọ;kò sí ohunkohun tí a lè fi wé e nínú ohun gbogbo tí ìwọ fẹ́.
16. Ẹ̀mí gígùn ń bẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀;ní ọwọ́ òsì rẹ̀ sì ni ọrọ̀ àti ọlá.