Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 28:16-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. Ọba tí ó jẹ gàba lórí ìlú láì gbàmọ̀ràn kò gbọ́nṣùgbọ́n ẹni tí ó kórìíra èrè ìjẹkújẹ yóò gbádùn ọjọ́ gígùn.

17. Ẹni tí ọkàn rẹ̀ kò balẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ìpànìyànyóò máa joró rẹ̀ títí ikúmá ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni ràn án lọ́wọ́.

18. Ẹni tí ìrìn rẹ̀ kò ní àbùkù wà láìléwuṣùgbọ́n ẹni tí ọ̀nà rẹ̀ jẹ́ ayípadà yóò ṣubú lójijì.

19. Ẹni tí ó bá ro ilẹ̀ rẹ̀ yóò ní oúnjẹ lọ́pọ̀lọpọ̀ṣùgbọ́n ẹni tí ń lé ohun aṣán yóò kún fún òsì.

20. Olóòótọ́ ènìyàn yóò rí ìbùkún gbà gan anṣùgbọ́n ẹni tí ojú ń kán láti di ọlọ́rọ̀ kì yóò lọ, láìjìyà.

21. Ojúṣááj ú ṣíṣe kò dáraṣíbẹ̀ ènìyàn kan ń ṣẹ̀ nítorí òkèlè oúnjẹ kan.

22. Ahun ń sáré àti làkò sì funra pé òsì dúró de òun.

23. Ẹni tí ó bá ènìyàn kan wí yóò rí ojú rere síi nígbẹ̀yìnju ẹni tí ó ní ètè ẹ̀tàn lọ.

24. Ẹni tí ó ja baba tàbí ìyá rẹ̀ lólètí ó sì wí pé “Kì í ṣe ẹ̀ṣẹ̀”irú kan ni òun àti ẹni tí ń panírun.

25. Ọ̀kanjúà ènìyàn a máa dá ìjà sílẹ̀,ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé Olúwa yóò gbilẹ̀.

26. Ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀lé ara rẹ̀ jẹ́ aláìgbọ́nṣùgbọ́n ẹni tí ń rìn nínú ọgbọ́n wà láìléwu.

27. Ẹni tí ó ń fifún talákà kì yóò ṣe aláìní ohunkóhunṣùgbọ́n ẹni tí ó di ojú rẹ̀ sí wọn gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ ègún.

28. Nígbà tí ènìyàn búburú bá dórí ìjọba, àwọn ènìyàn a na pápá bora;ṣùgbọ́n nígbà tí ènìyàn búburú bá ṣègbé,àwọn olódodo ń gbilẹ̀ síi.

Ka pipe ipin Òwe 28