Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 23:21-30 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

21. Nítorí pé ọ̀mùtí àti ọ̀jẹun ni yóò di talákà;ìmúni-tòògbé ní sì ń fi àkísà wọ ọkùnrin láṣọ.

22. Fetí sí ti baba rẹ tí ó bí ọ,má sì ṣe gan ìyá rẹ, nígbà tí o bá gbó

23. Ra òtítọ́, kí o má sì ṣe tà á;ra ọgbọ́n pẹ̀lú àti ẹ̀kọ́, àti òye.

24. Baba olódodo ni yóò yọ̀ gidigidi:ẹni tí ó sì bí ọmọ ọlọ́gbọ́n,yóò ní ayọ̀ nínú rẹ̀.

25. Jẹ́ kí bàbá rẹ àti ìyá rẹ ó yọ̀,sì jẹ́ kí inú ẹni tí ó bí ọ dùn.

26. Ọmọ mi, fi àyà rẹ fún mi,kí o sì jẹ́ kí ojú rẹ ní inú-dídùn sí ọ̀nà mi.

27. Nítorí pé panṣágà-obìnrin ọ̀gbun jínjìn ni;àti àjèjì-obìnrin kànga híhá ni.

28. Òun á sì ba ní bùba bí olè,a sì sọ àwọn olùrékọjá di púpọ̀ nínú àwọn ènìyàn.

29. Ta ni ó ni òsì? Ta ni ó ni ìbànújẹ́?Ta ni ó ni ìjà? Ta ni ó ni aṣọ̀? Ta ni ó ni ọgbẹ́ láìnídìí?

30. Àwọn tí ó dúró pẹ́ níbi ọtí-wáìnì;àwọn tí ń lọ láti dán ọtí wáìnì àdàlú wò.

Ka pipe ipin Òwe 23