Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 22:19-27 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Kí ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ lè wà níti Olúwa,èmi fi hàn ọ́ lónìí, àní fún ọ.

20. Èmi kò ha ti kọ̀wé ohun dáradárasí ọ níti ìmọ̀ràn àti níti ẹ̀kọ́,

21. Kí ó lè mú ọ mọ dídájú ọ̀rọ̀ òtítọ́;kí ìwọ le máa fi ìdáhùn òtítọ́ fún àwọn tí ó rán ọ?

22. Má ṣe ja talákà ní olè, nítorí tí ó jẹ́ talákà:bẹ́ẹ̀ ni kí o má sì ṣe ni olùpọ́njú lára ní ibodè:

23. Nítorí Olúwa yóò gbéjà wọn,yóò sì gba ọkàn àwọn tí ń gba tiwọn náà.

24. Má ṣe bá oníbìínu ènìyàn ṣe ọ̀rẹ́;má sì ṣe bá ọkùnrin onínú-fùfù rìn.

25. Kí ìwọ má ba à kọ́ ìwà rẹ̀,ìwọ a sì gba ìkẹ́kùn fún ara rẹ.

26. Má ṣe wà nínú àwọn tí ń ṣe ìgbọ̀wọ́,tàbí nínú àwọn tí ó dúró fún gbèsè.

27. Bí ìwọ kò bá ní nǹkan tí ìwọ ó fi ṣan,nítorí kín ni yóò ṣe gba ẹní rẹ kúrò lábẹ́ rẹ?

Ka pipe ipin Òwe 22