14. “Kò dára, kò dára” ní ẹni tó ra ọjà máa ń wínígbà tí ó bá kúrò níbẹ̀ tán, yóò máayangàn bí òun tí ṣe rí i rà sí.
15. Góòlù wà, iyùn sì wà rẹpẹtẹṣùgbọ́n, ahọ́n tí ń sọ ìmọ̀ gan an ni ọ̀ṣọ́ iyebíye.
16. Gba abọ́ ẹni tí ó ṣe onídùúró fún àlejò;mú un lọ́wọ́ bí ìbúra bí ó bá ṣe é fún obìnrin onírìnkurìn.
17. Oúnjẹ tí a fi ọ̀nà ẹ̀rú rí máa ń dùn lẹ́nu ènìyànṣùgbọ́n, a yọrí sí bi ẹnu tí ó kún fún èèpẹ̀.
18. Pa ètè rẹ mọ́ nípa wíwá ìmọ̀rànbí o bá ń jagun, gba ìtọ́ṣọ́nà.
19. Olófòófó dalẹ̀ àsírínítorí náà yẹra fún ènìyàn tí ń rojọ́ jù.
20. Bí ènìyàn kan bá ṣépè fún baba tàbí ìyá rẹ̀,ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ni a ó pa kú nínú òkùnkùn biribiri.
21. Ogún tí a kó jọ kíákíá ní ìbẹ̀rẹ̀kì yóò ní ìbùkún ní ìgbẹ̀yìn gbẹ́yín.
22. Má ṣe wí pé, “N ó ṣẹ̀ṣan àṣìṣe rẹ yìí fún ọ”Dúró de Olúwa yóò sì gbà ọ́ là.
23. Olúwa kórìíra òdiwọ̀n èké.Òṣùwọ̀n ìrẹ́jẹ kò sì tẹ́ ẹ lọ́rùn.
24. Olúwa ni ó ń ṣe olùdarí ìgbésẹ̀ ènìyànBáwo wá ni òye gbogbo ọ̀nà ènìyàn ṣe le yé ni?