Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 2:8-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. ó pa ipa ọ̀nà ìdájọ́ mọ́Ó sì ń pa ọ̀nà àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ mọ́.

9. Nígbà náà ni òye ohun tí ó tọ̀nà tí ó sì dára,tí ó dára yóò yẹ́ ọ—gbogbo ọ̀nà dídara.

10. Nítorí ọgbọ́n yóò wọ inú ọkàn rẹìmọ̀ yóò sì jẹ́ ìtura fún ọkàn rẹ

11. Ara (ikú) sísọ ni yóò dáàbò bò ọÒye yóò sì pa ọ́ mọ́.

12. Ọgbọ́n yóò gbà ọ́ là kúrò ní ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú,lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn tí ọrọ̀ ọ wọn jẹ́ àyídáyidà,

13. tí ó kúrò ní ọ̀nà tààràláti rìn ní ọ̀nà tí ó ṣókùnkùn,

14. tí ó ní inú dídùn sí ibi ṣíṣetí ó sì ń yayọ̀ nínú àyídáyidà ibi,

15. ọ̀nà àwọn tí ó ṣe pálapàlatí wọ́n sì jẹ́ alérekérekè ní ọ̀nà wọn.

16. Yóò gba ìwọ pẹ̀lú là kúrò lọ́wọ́ àwọn àgbèrè Obìnrinlọ́wọ́ aya oníwàkúwà àti àwọn ọ̀rọ̀ ìtànjẹ rẹ̀,

17. tí ó ti fi ọkọ àkọ́fẹ́ ìgbà èwe rẹ̀ sílẹ̀tí ó sì gbàgbé májẹ̀mú tí ó ti dá níwájú Ọlọ́run.

18. Nítorí ilé rẹ̀ jẹ́ ọ̀nà sí ikúọ̀nà rẹ̀ sì lọ sí ibi ẹ̀mí àwọn òkú.

Ka pipe ipin Òwe 2