Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 2:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ọmọ mi, bí ìwọ bá gba ọ̀rọ̀ mi,tí ìwọ sì pa òfin mi mọ́ sí inú rẹ,

2. tí o tẹ́ etí rẹ sílẹ̀ sí ọgbọ́ntí o sì fi ọkàn rẹ sí òye,

3. bí ìwọ sì pè fún ojú inú rẹ rírantí o sì kígbe sókè fún òye

4. bí ìwọ bá wá ṣàfẹ́rì rẹ̀ bí i fàdákàtí o sì wa kiri bí i fún ohun iyebíye tó fara sin.

5. Nígbà náà ni òye ẹ̀rù Olúwa yóò yé ọ,tí ó sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run.

6. Nítorí Olúwa ni ó ń fún ni ní ọgbọ́n,láti ẹnu rẹ̀ sì ni ìmọ̀ àti òye ti ń wá

7. Ó to ìgbàlà fún àwọn olódodo,Òun ni aṣà fún àwọn tí ń rìn déédé,

8. ó pa ipa ọ̀nà ìdájọ́ mọ́Ó sì ń pa ọ̀nà àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ mọ́.

Ka pipe ipin Òwe 2