1. Ọmọ mi, bí ìwọ bá gba ọ̀rọ̀ mi,tí ìwọ sì pa òfin mi mọ́ sí inú rẹ,
2. tí o tẹ́ etí rẹ sílẹ̀ sí ọgbọ́ntí o sì fi ọkàn rẹ sí òye,
3. bí ìwọ sì pè fún ojú inú rẹ rírantí o sì kígbe sókè fún òye
4. bí ìwọ bá wá ṣàfẹ́rì rẹ̀ bí i fàdákàtí o sì wa kiri bí i fún ohun iyebíye tó fara sin.
5. Nígbà náà ni òye ẹ̀rù Olúwa yóò yé ọ,tí ó sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run.