Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 14:23-35 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

23. Gbogbo iṣẹ́ àṣekára ló máa ń mú èrè wáṣùgbọ́n ẹjọ́ rírò lásán máa ń ta ni lósì ni.

24. Ọrọ̀ Ọlọgbọ́n ènìyàn ni adé orí wọnṣùgbọ́n ìwà aláìgbọ́n ń mú ìwà òmùgọ̀ wá.

25. Ẹlẹ́rìí tí ó ṣòótọ́ gba ẹ̀mí làṣùgbọ́n ẹlẹ́rìí èké jẹ́ ẹlẹ́tàn.

26. Ẹni tí ó bẹ̀rù Olúwa ni ilé ìṣọ́ ààbòyóò sì tún jẹ́ ààbò fún àwọn ọmọ rẹ̀.

27. Ìbẹ̀rù Olúwa jẹ́ oríṣun ìyè,tí ń yí ènìyàn padà kúrò nínú ìkẹ́kùn ikú.

28. Ènìyàn púpọ̀ ní ìlú jẹ́ ògo Ọba,ṣùgbọ́n láì sí ìjòyè, Ọba á parun.

29. Onísùúrù ènìyàn ní òye tí ó pọ̀,ṣùgbọ́n onínú fùfù ènìyàn máa ń fi ìwà aṣiwèrè hàn.

30. Ọkàn tí ó lálàáfíà fi ìyè mú kí ọjọ́ ayé gùn fún ara,ṣùgbọ́n ìlara mú kí egungun jẹrà.

31. Ẹni tí ó fi ìyà jẹ aláìní ń fi ìkórìíra hànṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó ṣoore fún aláìní bu ọlá fún Ọlọ́run.

32. Nígbà tí ìyọnu bá dé, a fa àwọn búburú lulẹ̀,kódà nínú ikú àwọn olódodo ni ààbò.

33. Ọgbọ́n wà nínú ọkàn olóyekódà láàrin àwọn aláìlóye, ó jẹ́ kí wọn mọ òun.

34. Ododo a máa gbé orílẹ̀ èdè ga,ṣùgbọ́n ìtìjú ni ẹ̀ṣẹ̀ jẹ́ fún àwùjọ káwùjọ.

35. Ọba a máa ní inú dídùn sí ìránṣẹ́ tí ó gbọ́nṣùgbọ́n ìbínú rẹ̀ wá sórí ìránṣẹ́ adójútini.

Ka pipe ipin Òwe 14