Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 14:14-33 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. A ó san án lẹ́kùnrẹ́rẹ́ fún aláìgbàgbọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀Ènìyàn rere yóò sì gba èrè fún tirẹ̀.

15. Òpè ènìyàn gba ohun gbogbo gbọ́ṣùgbọ́n Olóye ènìyàn ronú lórí àwọn ìgbéṣẹ̀ rẹ̀.

16. Ọlọgbọ́n bẹ̀rù Ọlọ́run ó sì kórìíra ibiṣùgbọ́n aláìgbọ́n jẹ́ alágídí àti aláìṣọ́ra.

17. Ẹni tí ó máa ń tètè bínú máa ń hùwà aṣiwèrè,a sì kórìíra eléte ènìyàn:

18. Òpè jogún ìwà òmùgọ̀ṣùgbọ́n a dé ọlọgbọ́n ní adé ìmọ̀.

19. Ènìyàn ìkà yóò tẹríba níwájú àwọn ènìyàn rereàti ènìyàn búburú níbi ìlẹ̀kùn àwọn olódodo.

20. Kódà àwọn aládùúgbò o talákà kò fẹ́ràn rẹ̀ṣùgbọ́n, Ọlọ́rọ̀ ní ọ̀rẹ́ púpọ̀.

21. Ẹni tí ó kẹ́gàn aládùúgbò o rẹ̀ ti dẹ́ṣẹ̀ṣùgbọ́n ìbùkún ni fún ẹni tí ó ṣàánú àwọn aláìní.

22. Ǹjẹ́ àwọn tí ń pète ibi kì í sìnà?Ṣùgbọ́n àwọn tí ń gbérò ohun rere ń rí ìfẹ́ àti òtítọ́.

23. Gbogbo iṣẹ́ àṣekára ló máa ń mú èrè wáṣùgbọ́n ẹjọ́ rírò lásán máa ń ta ni lósì ni.

24. Ọrọ̀ Ọlọgbọ́n ènìyàn ni adé orí wọnṣùgbọ́n ìwà aláìgbọ́n ń mú ìwà òmùgọ̀ wá.

25. Ẹlẹ́rìí tí ó ṣòótọ́ gba ẹ̀mí làṣùgbọ́n ẹlẹ́rìí èké jẹ́ ẹlẹ́tàn.

26. Ẹni tí ó bẹ̀rù Olúwa ni ilé ìṣọ́ ààbòyóò sì tún jẹ́ ààbò fún àwọn ọmọ rẹ̀.

27. Ìbẹ̀rù Olúwa jẹ́ oríṣun ìyè,tí ń yí ènìyàn padà kúrò nínú ìkẹ́kùn ikú.

28. Ènìyàn púpọ̀ ní ìlú jẹ́ ògo Ọba,ṣùgbọ́n láì sí ìjòyè, Ọba á parun.

29. Onísùúrù ènìyàn ní òye tí ó pọ̀,ṣùgbọ́n onínú fùfù ènìyàn máa ń fi ìwà aṣiwèrè hàn.

30. Ọkàn tí ó lálàáfíà fi ìyè mú kí ọjọ́ ayé gùn fún ara,ṣùgbọ́n ìlara mú kí egungun jẹrà.

31. Ẹni tí ó fi ìyà jẹ aláìní ń fi ìkórìíra hànṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó ṣoore fún aláìní bu ọlá fún Ọlọ́run.

32. Nígbà tí ìyọnu bá dé, a fa àwọn búburú lulẹ̀,kódà nínú ikú àwọn olódodo ni ààbò.

33. Ọgbọ́n wà nínú ọkàn olóyekódà láàrin àwọn aláìlóye, ó jẹ́ kí wọn mọ òun.

Ka pipe ipin Òwe 14