Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 12:8-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. A ń yín ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀n ọgbọ́n rẹ̀ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn ọlọ́pọlọ wúruwùru ni a kẹ́gàn.

9. Ó sàn kí a má jẹ́ ènìyàn pàtàkì kí a sì ní ìránṣẹ́ju kí a díbọ́n pé a jẹ́ ẹni pàtàkì láì lóúnjẹ.

10. Ènìyàn rere ń ṣaájò ohun tí àwọn ohun ọ̀sìn rẹ̀ nílòÀmọ́ ìwà tó dára jù tí ènìyàn búburú lè hù, ibi ni.

11. Ẹni tí ó bá dáko yóò ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ oúnjẹ,ṣùgbọ́n ẹni tí ń lépa òjìji lásánlàsàn kò gbọ́n.

12. Ènìyàn búburú ń fẹ́ ìkógún àwọn ènìyàn ìkàṣùgbọ́n gbòǹgbò Olódodo ń gbilẹ̀.

13. A mú ènìyàn búburú nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ ẹsẹ̀ rẹ̀ṣùgbọ́n Olódodo bọ́ kúrò lọ́wọ́ ìdàámú.

14. Láti inú èso rẹ̀, ènìyàn kún fún onírúurú ohun rerebí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ti ń pín in lérè dájúdájú.

15. Ọ̀nà aláìgbọ́n dára lójú ara rẹ̀ṣùgbọ́n Ọlọgbọ́n ènìyàn a máa gba ìmọ̀ràn.

16. Aláìgbọ́n ènìyàn fi ìbínú un rẹ̀ hàn lẹ́ṣẹ̀kẹṣẹ̀,ṣùgbọ́n olóye ènìyàn fojú fo ìyànjẹ.

17. Ẹni tí ó jẹ́ ajẹ́rìí tòótọ́ jẹ́rìí ohun tí ojú rẹ̀ ríṣùgbọ́n ajẹ́rìí èké máa ń parọ́.

18. Ọ̀rọ̀ tí a kò rò jinlẹ̀ máa ń gún ni bí ọ̀kọ̀ṣùgbọ́n ahọ́n ọlọgbọ́n ń mú ìwòsàn wá.

19. Ètè tí ń sòótọ́ yóò wà láéláéṣùgbọ́n ahọ́n tí ń parọ́ kì í tọ́jọ́.

20. Ẹ̀tàn wà nínú ọkàn àwọn tí ń pète búburúṣùgbọ̀n ayọ̀ wà fún àwọn tí ń mú kí àlàáfíà gbilẹ̀.

21. Ibi kì í ṣubú lu Olódodo ráráṣùgbọ́n ènìyàn búburú gba ìpín ìyọnu tiwọn.

22. Olúwa kóìríra ètè tí ń parọ́ṣùgbọ́n ó ní inú dídùn sí àwọn Olóòótọ́.

23. Ènìyàn Olóye fi ìmọ̀ rẹ̀ pamọ́ sínú ara rẹ̀ṣùgbọ́n ọkàn ènìyàn búburú ń gbé ìwà òmùgọ̀ jáde.

24. Ọwọ́ àìṣọ̀lẹ yóò jọbaṣùgbọ́n ọ̀lẹ ṣíṣe a máa yọrí sí sínsìnrú.

25. Ìbànújẹ́ ní ọkàn ènìyàn ní dorí rẹ̀ kodòṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ rere a máa mú kó yọ̀.

26. Olódodo ènìyàn máa ń ṣọ́ra láti dọ́rẹ̀ẹ́ṣùgbọ́n ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú ń mú wọn sìnà.

Ka pipe ipin Òwe 12