Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 11:5-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Òdodo aláìlẹ́gàn ṣe ọ̀nà tààrà fún wọnṣùgbọ́n ìwà búburú ènìyàn búburú yóò fàá lulẹ̀.

6. Òdodo ẹni ìdúró ṣinṣin gbà wọ́n làṣùgbọ́n ìdẹkùn ètè búburú mú aláìsòótọ́.

7. Nígbà tí ènìyàn búburú bá kú, ìrètí rẹ̀ a parungbogbo ohun tó ń fojú sọ́nà fún nípa agbára rẹ̀ já sófo.

8. A gba olódodo kúrò lọ́wọ́ ibidípò o rẹ̀, ibi wá sórí ènìyàn búburú.

9. Aláìmọ̀ Ọlọ́run fi ẹnu rẹ̀ ba aládùúgbò rẹ̀ jẹ́,ṣùgbọ́n nípasẹ̀ ìmọ̀ Olódodo sá àsálà.

10. Nígbà tí Olódodo ń gbèrú, ìlú a yọ̀nígbà tí ènìyàn búburú parun, ariwo ayọ̀ gba ìlú kan.

11. Nípaṣẹ̀ ìbùkún, Olódodo a gbé ìlú ga:ṣùgbọ́n nípaṣẹ̀ ẹnu ènìyàn búburú, a pa ìlú run.

12. Ẹni tí kò gbọ́n fojú kékeré wo aládùúgbò rẹ̀ṣùgbọ́n ẹni tí ó ní òye pa ẹnu rẹ̀ mọ́.

Ka pipe ipin Òwe 11