Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 10:20-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

20. Ètè Olódodo jẹ́ àṣàyan fàdákàṣùgbọ́n ọkàn ènìyàn buburú kò níye lórí.

21. Ètè Olódodo ń bọ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ṣùgbọ́n aláìgbọ́n ń kú nítorí àìlóye.

22. Ìbùkún Olúwa ń mú ọrọ̀ wá,kì í sìí fi ìdàámú sí i.

23. Aláìgbọ́n a máa ní inú dídùn sí ìwà búburúṣùgbọ́n olóye ènìyàn a máa ní inú dídùn sí ọgbọ́n.

24. Ohun tí ènìyàn búburú bẹ̀rù yóò dé bá a;Olódodo yóò rí ohun tí ó fẹ́ gbà.

25. Nígbà tí ìjì bá ti jà kọjá, ènìyàn búburú a kọjá lọ,ṣùgbọ́n Olódodo yóò dúró ṣinṣin láéláé.

26. Bí ọtí kíkan sí eyín, àti èéfín sí ojúbẹ́ẹ̀ ni ọ̀lẹ sí ẹni tí ó rán an níṣẹ́.

Ka pipe ipin Òwe 10