Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 10:19-25 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Nínú ọ̀rọ̀ púpọ̀ a kò le fẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ kùṣùgbọ́n ẹni tí ó pa ẹnu rẹ̀ mọ́ jẹ́ ọlọ́gbọ́n.

20. Ètè Olódodo jẹ́ àṣàyan fàdákàṣùgbọ́n ọkàn ènìyàn buburú kò níye lórí.

21. Ètè Olódodo ń bọ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ṣùgbọ́n aláìgbọ́n ń kú nítorí àìlóye.

22. Ìbùkún Olúwa ń mú ọrọ̀ wá,kì í sìí fi ìdàámú sí i.

23. Aláìgbọ́n a máa ní inú dídùn sí ìwà búburúṣùgbọ́n olóye ènìyàn a máa ní inú dídùn sí ọgbọ́n.

24. Ohun tí ènìyàn búburú bẹ̀rù yóò dé bá a;Olódodo yóò rí ohun tí ó fẹ́ gbà.

25. Nígbà tí ìjì bá ti jà kọjá, ènìyàn búburú a kọjá lọ,ṣùgbọ́n Olódodo yóò dúró ṣinṣin láéláé.

Ka pipe ipin Òwe 10