Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 10:13-31 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Ọgbọ́n ni a ń bá lẹ́nu àwọn olóyeṣùgbọ́n kùmọ wà fún ẹ̀yìn àwọn aláìlóye.

14. Ọlọ́gbọ́n ènìyàn kó ìmọ̀ jọṣùgbọ́n ẹnu aláìgbọ́n a máa ṣokùnfà ìparun.

15. Ọrọ̀ àwọn Olódodo ni ìlú olódi wọn,ṣùgbọ́n òsì ni ìparun aláìní.

16. Èrè Olódodo ń mú ìyè wá fún wọnṣùgbọ́n èrè ènìyàn búburú ń mú ìjìyà wá fún wọn.

17. Ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí fi ọ̀nà sí ìyè hànṣùgbọ́n ẹni tí ó kọ ìbáwí mú àwọn mìíràn sìnà.

18. Ẹni tí ó pa ìkórìíra rẹ̀ mọ́ jẹ́ òpùrọ́ẹni tí ó sì ń báni jẹ́ jẹ́ aláìgbọ́n.

19. Nínú ọ̀rọ̀ púpọ̀ a kò le fẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ kùṣùgbọ́n ẹni tí ó pa ẹnu rẹ̀ mọ́ jẹ́ ọlọ́gbọ́n.

20. Ètè Olódodo jẹ́ àṣàyan fàdákàṣùgbọ́n ọkàn ènìyàn buburú kò níye lórí.

21. Ètè Olódodo ń bọ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ṣùgbọ́n aláìgbọ́n ń kú nítorí àìlóye.

22. Ìbùkún Olúwa ń mú ọrọ̀ wá,kì í sìí fi ìdàámú sí i.

23. Aláìgbọ́n a máa ní inú dídùn sí ìwà búburúṣùgbọ́n olóye ènìyàn a máa ní inú dídùn sí ọgbọ́n.

24. Ohun tí ènìyàn búburú bẹ̀rù yóò dé bá a;Olódodo yóò rí ohun tí ó fẹ́ gbà.

25. Nígbà tí ìjì bá ti jà kọjá, ènìyàn búburú a kọjá lọ,ṣùgbọ́n Olódodo yóò dúró ṣinṣin láéláé.

26. Bí ọtí kíkan sí eyín, àti èéfín sí ojúbẹ́ẹ̀ ni ọ̀lẹ sí ẹni tí ó rán an níṣẹ́.

27. Ìbẹ̀rù Olúwa ń mú ọjọ́ ayé gígùn wá,ṣùgbọ́n a gé ojọ́ ayé ènìyàn búburú kúrú.

28. Ìrètí Olódodo ni ayọ̀ṣùgbọ́n ìrètí ènìyàn buburú já sí òfo.

29. Ọ̀nà Olúwa jẹ́ ààbò fún Olódodo,ṣùgbọ́n ìparun ni ó jẹ́ fún àwọn tí ń se ibi.

30. A kì yóò fa Olódodo tu láéláéṣùgbọ́n ènìyàn buburú kì yóò dúró pẹ́ lórí ilẹ̀.

31. Ẹnu Olódodo ń mú ọgbọ́n jáde wá,ṣùgbọ́n ètè àyípadà ni a ó gé kúrò.

Ka pipe ipin Òwe 10