Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 1:20-32 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

20. Ọgbọ́n kígbe sókè ní pópóó gbé ohùn rẹ̀ sókè láàrin ọjà;

21. Láàrin ọjà ni ó ti kígbe jádeNí ibodè ìlú ni ó ti sọ̀rọ̀ ọ rẹ̀:

22. “Yóò ha ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin aláìmọ́kan yóò fi fẹ́ àìmọ̀kan yín tó?Yóò ha ti pẹ́ tó tí àwọn ẹlẹ́gàn yóò ṣe inú dídùn sí ìpẹ̀gàn tó?Àwọn aláìgbọ́n kórìíra ìmọ̀?

23. Bí ẹ bá ti gbọ́ ìbáwí ì mi ni,Ǹ bá ti tú ohun tí ó wà nínú ọkàn mi jáde fún yínkí n sì fi inú un mi hàn sí i yín.

24. Ṣùgbọ́n níwọ̀n bí ẹ ti kọ ìpè ní ìgbà tí mo pèkò sì sí ẹni tí ó kọ ibi ara sí mi gbà tí mo háwọ́ sí wọn,

25. Níwọ̀n bí ẹ ti kọ gbogbo ìmọ̀ràn mití ẹ kò sì ní gba ìbáwí mi

26. Èmi pẹ̀lú yóò fi ìdààmú yín rẹ́rìn-ínN ó sẹ̀fẹ̀ nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín

27. Nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín bí ìjì líle,Nígbà tí ìdàámú bá dé bá ọ bí ààjà,nígbà tí wàhálà àti ìbànújẹ́ ọkàn bá bò ọ́ mọ́lẹ̀.

28. “Nígbà náà ni wọn yóò ké pè mí ṣùgbọ́n, èmi kò ní dáhùn;wọn yóò farabalẹ̀ wá mi ṣùgbọ́n wọn kì yóò rí mi.

29. Níwọ̀n bí wọ́n ti kórìíra ìmọ̀tí wọ́n sì kọ̀ láti bẹ̀rù Olúwa.

30. Níwọ̀n bí wọn kò ti gbà ìmọ̀ràn mití wọ́n sì kẹ́gàn ìmọ̀ràn mi,

31. Wọn yóò jẹ èrè iṣẹ́ ọwọ́ wọnwọn yóò sì jèrè èso ètè wọn ní kíkún

32. Nítorí ìrìnkurìn àwọn aláìmọ́kan ni yóò pa wọ́nìkáwọ́-gbera aláìgbọ́n ni yóò pa á run;

Ka pipe ipin Òwe 1