Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 1:1-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Àwọn òwe ti Sólómónì, ọmọ Dáfídì, ọba Ísírẹ́lì.

2. Láti le ní ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́Láti ní òye àwọn ọ̀rọ̀ ìjìnlẹ̀

3. Láti ní ẹ̀kọ́ àti gbé ìgbé ayé ìkíyèsára,láti ṣe ohun tí ó tọ́, àti òdodo tí ó sì dára

4. láti fún onírẹ̀lẹ̀ ní ìkíyèsáraìmọ̀ àti ìṣọ́ra fún àwọn èwe

5. Jẹ́ kí Ọlọgbọ́n tẹ́tí kí ó sì ní ìmọ̀ kún ìmọ̀,sì jẹ́ kí ẹni òye gba ìtọ́sọ́nà

6. láti mọ ìtumọ̀ òwe àti ìtàn-dòwe, (àlọ́ onítàn)àwọn ọ̀rọ̀ àti àlọ́ àwọn Ọlọgbọ́n.

7. Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìbẹ̀rẹ̀ ìmọ̀,ṣùgbọ́n aláìgbọ́n kẹ́gàn ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́.

8. Tẹ́tí, ìwọ ọmọ mi sí ẹ̀kọ́ baba rẹmá ṣe kọ ẹ̀kọ́ màmá ọ̀ rẹ sílẹ̀

9. Wọn yóò jẹ́ òdòdó ẹ̀yẹ olóòrùn dídùn lórí rẹàti ọ̀ṣọ́ tí ó dára yí ọrùn rẹ ká.

10. Ọmọ mi, bí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ bá ń tàn ọ́,má ṣe gbà fún wọn.

11. Bí wọn bá wí pé, “Tẹ̀lé wa kálọ;jẹ́ ká ba ní ibùba fún ẹ̀jẹ̀ ẹnìkan,jẹ́ ká dá àwọn aláìlera kan lọ́nà;

Ka pipe ipin Òwe 1