Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Sólómónì 6:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Níbo ni olùfẹ́ rẹ lọ,Ìwọ arẹwà jùlọ láàárin àwọn obìnrin?Níbo ni olùfẹ́ rẹ yà sí,kí a lè bá ọ wá a?

2. Olùfẹ́ mi ti ṣọ̀kalẹ̀ lọ sínú ọgbà rẹ̀,sí ibi ibùsùn tùràrí,láti máa jẹ nínú ọgbàláti kó ìtànná lílì jọ.

3. Èmi ni ti olùfẹ́ mi, olùfẹ́ mi sì ni tèmi,Ó ń jẹ láàárin ìtànná lílì,

4. Ìwọ lẹ́wà olùfẹ́ mi, bí i Tírísà,Ìwọ lẹ́wà bí i Jérúsálẹ́mù,ìwọ lẹ́rù bí ogun pẹ̀lú ọ̀págun.

Ka pipe ipin Orin Sólómónì 6