Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Oníwàásù 9:14-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Ìlú kékeré kan tí ènìyàn díẹ̀ wà nínú rẹ̀ wà ní ìgbà kan rí. Ọba alágbára kan sì ṣígun tọ ìlú náà lọ, ó yìí po, ó sì kọ́ ilé-ìṣọ́ tí ó tóbi lòdì síi.

15. Ṣùgbọ́n, tálákà ọkùnrin tí ó jẹ ọlọgbọ́n kan ń gbé ní ìlú náà, ó sì gba gbogbo ìlú u rẹ̀ là pẹ̀lú ọgbọ́n-ọn rẹ̀. Ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó rántí ọkùnrin talákà náà.

16. Nítorí náà mo ṣọ wí pé “Ọgbọ́n dára ju agbára.” Ṣùgbọ́n a kẹ́gàn ọgbọ́n ọkùnrin talákà náà, wọn kò sì mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣe.

17. Ọ̀rọ̀ pẹ̀lẹ́ ọlọgbọ́n ènìyàn a máa wà ní ìmú ṣeju igbe òmùgọ̀ alákòóso lọ.

18. Ọgbọ́n dára ju ohun—èlò ogun lọ,ṣùgbọ́n ẹlẹ́ṣẹ̀ kan a máa ba ohun dídára púpọ̀ jẹ́.

Ka pipe ipin Oníwàásù 9