Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Oníwàásù 4:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Mo sì tún wò ó, mo sì ri gbogbo ìnilára tí ó ń ṣẹlẹ̀ lábẹ́ oòrùn:mo rí ẹkún àwọn tí ara ń ni, wọn kòsì ní Olùtùnú kankan,agbára wà ní ìkápá àwọn tí ó ń ni wọ́n lárawọn kò sì ní olùtùnú kankan.

2. Mo jowú àwọn tí wọ́n ti kútí wọ́n sì ti lọ,ó ṣàn fún wọn ju àwọntí wọ́n sì wà láàyè lọ.

3. Nítòótọ́, ẹni tí kò tí ì sí sàn juàwọn méjèèjì lọ:ẹni tí kò tí ì rí iṣẹ́ búburútí ó ń lọ ní abẹ́ oòrun.

4. Mo sì tún mọ̀ pẹ̀lú, ìdí tí ènìyàn fi ń ṣiṣẹ́ tagbáratagbára láti ṣe àṣeyọrí, nítorí pé wọn ń jowú àwọn aládùgbò wọn ni. Ṣùgbọ́n, aṣán ni, ó dàbí ẹni ń gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́.

5. Aṣiwèrè ká ọwọ́ rẹ̀ kòó sì ba tara rẹ̀ jẹ́.

Ka pipe ipin Oníwàásù 4