Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Oníwàásù 10:16-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. Ègbé ni fún ọ, ìwọ ilẹ̀ tí ọba ń ṣe ìranṣẹ́ rẹ̀àti tí àwọn ọmọ aládé ń ṣe àsè ní òwúrọ̀.

17. Ìbùkún ni fún ọ, ìwọ ilẹ̀ èyí tí ọba rẹ̀ jẹ́ọmọ ọlọ́lá, àti tí àwọn ọmọ aládé ń jẹun ní àsìkò tí ó yẹ,fún ìlera, tí kì í ṣe fún ìmọ̀tí para.

18. Bí ènìyàn bá ń lọ́ra, ilé a máa wú,bí ọwọ́ rẹ̀ bá ń ṣe ọ̀lẹ, ilé a máa jó.

19. Ẹ̀rín rínrín ni a ṣe àṣè fún,wáìnì a máa mú ayé dùn,ṣùgbọ́n owó ni ìdáhùn sí ohun—gbogbo.

20. Ma ṣe bú ọba, kódà nínú èrò rẹ,tàbí kí o ṣépè fún ọlọ́rọ̀ ní ibi ìbùsùn rẹ,nítorí pé ẹyẹ ojú—ọ̀run le è gbé ọ̀rọ̀ rẹẹyẹ tí ó sì ní ìyẹ́ apá le è fi ẹjọ́ ohun tí o sọ sùn.

Ka pipe ipin Oníwàásù 10