Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Onídájọ́ 21:8-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Wọ́n sì béèrè wí pé, “È wo ni nínú ẹ̀yà Ísírẹ́lì ni ó kọ̀ láti bá àwọn ènìyàn péjọ níwájú Olúwa ní Mísípà?” Wọ́n ríì pé kò sí ẹnìkankan tí ó wa láti Jabesi-Gílíádì tí ó wá sí ibùdó fún àjọ náà.

9. Nítorí pé nígbà tí wọ́n ka àwọn ènìyàn, wọ́n rí i pé kò sí ẹnìkan kan láti inú àwọn ará Jabesi-Gílíádì tí ó wà níbẹ̀.

10. Àwọn ìjọ ènìyàn náà sì rán ẹgbàá mẹ́fà àwọn jagunjagun ọkùnrin, lọ sí Jabesi Gílíádì wọ́n fún wọn ní àṣẹ pé, ẹ lọ fi idà kọlu gbogbo àwọn tí ó wà níbẹ̀, pẹ̀lú àwọn obìnrin àti àwọn ọmọ wẹ́wẹ́.

11. Wọ́n ní, “Èyí ni ẹ̀yin yóò ṣe, ẹ pa gbogbo ọkùnrin àti gbogbo obìnrin tí kì í ṣe wúndíá.”

12. Wọ́n rí àwọn irinwó (400) ọ̀dọ́bìnrin tí kò mọ ọkùnrin rí nínú àwọn olùgbé Jabesi-Gílíádì, wọ́n sì mú wọn lọ sí ibùdó ní Ṣílò àwọn ará Kénánì.

13. Gbogbo ìjọ àwọn ènìyàn sì ránṣẹ́ àlàáfíà sí àwọn Bẹ́ńjámínì ní ihò àpáta Rímónì.

14. Àwọn ẹ̀yà Bẹ́ńjámínì náà sì padà ní àkókò náà, wọ́n sì fún wọn ní àwọn obìnrin Jabesi Gílíádì. Ṣùgbọ́n wọn kò kárí gbogbo wọn.

15. Àwọn ènìyàn náà sì káàánú nítorí ẹ̀yà Bẹ́ńjámínì, nítorí Olúwa fi àlàfo kan sílẹ̀ nínú àwọn ẹ̀yà Ísírẹ́lì.

16. Àwọn olórí ìjọ àwọn ènìyàn náà wí pé, “Kí ni àwa yóò ṣe láti rí aya fún àwọn ọkùnrin tí ó kù nígbà tí a ti pa gbogbo àwọn obìnrin Bẹ́ńjámínì run?”

Ka pipe ipin Onídájọ́ 21