Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 7:10-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Nígbà tí a ta òróró sórí pẹpẹ. Àwọn olórí mú àwọn ọrẹ wọn wá fún ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀, wọ́n sì kó wọn wá ṣíwájú pẹpẹ.

11. Nítorí tí Olúwa ti sọ fún Mósè pé, “Olórí kọ̀ọ̀kan ní ọjọ́ kọ̀ọ̀kan ni yóò máa mú ọrẹ tirẹ̀ wá ṣíwájú pẹpẹ.”

12. Ẹni tí ó mú ọrẹ tirẹ̀ wá ní ọjọ́ kìn-ín-ni Náṣónì ọmọ Ámínádábù láti inú ẹ̀yà Júdà.

13. Ọrẹ rẹ̀ jẹ́ àwo fàdákà kan tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ àádóje (130) ṣékélì àti àwokòtò ti fàdákà tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ àádọ́rin (70) ṣékélì, méjèèjì gẹ́gẹ́ bí iye owó ibi mímọ́ àwo kọ̀ọ̀kan kún fún ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára tí a fi òróró pò gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ohun jíjẹ;

14. Àwo wúrà kan tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ ṣékélì mẹ́wàá tí ó kún fún tùràrí;

15. Ọ̀dọ́ akọ màlúù kan, àgbò kan, akọ ọ̀dọ́ àgùntàn ọlọ́dún kan fún ẹbọ sísun,

16. Akọ ewurẹ́ kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀,

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 7