Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 32:30-36 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

30. Ṣùgbọ́n tí wọn kò bá fẹ́ bá yín rékọjá pẹ̀lú ìhámọ́ra, wọn gbọdọ̀ gba ìní wọn pẹ̀lú yín ní Kénánì.”

31. Àwọn ọmọ Gádì àti ọmọ Rúbẹ́nì dáhùn pé, “Iránṣẹ́ rẹ yóò ṣe ohun tí Olúwa ti sọ.

32. A máa rékọjá níwájú Olúwa lọ sí Kénánì pẹ̀lú ìhámọ́ra, ṣùgbọ́n ẹrù tí a jogún yóò wà ní ẹ̀bá Jọ́dánì.”

33. Nígbà náà Mósè fún àwọn ọmọ Gádì àti àwọn ọmọ Rúbẹ́nì àti ààbọ̀ ẹ̀yà Mánásè ọmọ Jóṣẹ́fù ìjọba Ṣíhónì ọba àwọn ọmọ Ámórì àti ìjọba Ógù ọba Básánì ní gbogbo ilẹ̀ náà pẹ̀lú ìlú rẹ̀ àti agbégbé tí ó yí i ka.

34. Àwọn ará Gádì wọ́n kọ́ Dídónì, Átarótù, Áróérì;

35. Pẹ̀lú Átírótù Ṣófánì, Jásérì, àti Jógbénà:

36. Pẹ̀lú Bétínímírà, àti Bétí-Áránì ìlú olódi, àti agbo fún àgùntàn.

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 32