Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 32:1-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Àwọn ọmọ Rúbẹ́nì àti àwọn ọmọ Gádì, tí wọ́n ní ẹran ọ̀sìn àti ohun ọ̀sìn rí wí pé ilé Jásérì àti Gádì dára fún ohun ọ̀sìn.

2. Nígbà náà wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ Mósè àti Élíásárì àlùfáà àti sí olórí gbogbo ìlú, wọ́n sì wí pé,

3. “Átarótì, Díbónì, Jásérì, Nímírà, Hésíbónì, Élíálì, Sébámù, Nébò, àti Béónì.

4. Ni ilẹ̀ tí Olúwa ti ṣẹ́gun níwájú àwọn ènìyàn Ísírẹ́lì tí ó sì dára fún ohun ọ̀sìn, ṣáwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì ní ohun ọ̀sìn.

5. Tí a bá rí ojú rere rẹ,” wọ́n wí, “jẹ́ kí a fi ilẹ̀ yìí fún ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ìní. Má se jẹ́kí a rékọjá odò Jọ́dánì.”

6. Mósè sọ fún àwọn ọmọ Gádì àti fún ọmọ Rúbẹ́nì pé, “Ṣé kí àwọn arákùnrin yín lọ sí ogun, kí ẹ̀yin kí ó sì jókó sí bí?

7. Kí ni ó dé tí o fi mú ìrẹ̀wẹ̀sì bá àwọn ọmọ Ísírẹ́lì láti lọ sí ibi ilẹ̀ tí Olúwa ti fi fún wọn?

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 32