Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 3:7-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Wọn yóò máa ṣiṣẹ́ fún un àti fún gbogbo ìjọ ènìyàn ní Àgọ́ Ìpàdé bí wọ́n ti ń ṣiṣẹ́ ìsìn nínú àgọ́.

8. Wọn yóò máa tọ́jú gbogbo ohun èlò inú Àgọ́ Ìpàdé, wọn yóò sì máa ṣe ojúṣe àwọn ọmọ Ísírẹ́lì nípa ṣíṣe iṣẹ́ nínú àgọ́.

9. Fi ẹ̀yà Léfì jìn Árónì àti àwọn ọmọ rẹ̀, àwọn nìkan ni a fi fún Árónì nínú gbogbo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.

10. Kí o sì yan Árónì àti àwọn ọmọ rẹ̀ láti máa ṣiṣẹ́ àlùfáà; ẹnikẹ́ni tó bá súnmọ́ ibi mímọ́ pípa ni kí ẹ pa á.”

11. Olúwa tún sọ fún Mósè pé,

12. “Báyìí èmi fúnra mi ti mú ẹ̀yà Léfì láàrin àwọn ọmọ Ísírẹ́lì dípò gbogbo àkọ́bí ọkùnrin àwọn ọmọbìnrin Ísírẹ́lì. Ti èmi ni àwọn ọmọ Léfì,

13. nítorí pé ti èmi ni gbogbo àkọ́bí. Ní ọjọ́ tí mo pa gbogbo àkọ́bí ní ilẹ̀ Éjíbítì ni mo ti ya gbogbo àkọ́bí sọ́tọ̀ ní Ísírẹ́lì yálà ti ènìyàn tàbí ti ẹranko. Gbogbo wọn gbọdọ̀ jẹ́ ti èmi. Èmi ni Olúwa.”

14. Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mósè ní ihà Ṣínáì pé,

15. “Ka àwọn ọmọ Léfì nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn kí o ka gbogbo ọmọkùnrin láti ọmọ oṣù kan sókè”

16. Mósè sì kà wọ́n gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa ti pa á láṣẹ fún un.

17. Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Léfì:Gáṣónì, Kóhátì àti Mérárì.

18. Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Gáṣónì:Líbínì àti Ṣíméhì.

19. Àwọn ìdílé Kóhátì ni:Ámírámù, Ísíhárì, Hébírónì àti Yúsíélì.

20. Àwọn ìdílé Mérárì ni:Málì àti Músì.Wọ̀nyí ni ìdílé Léfì gẹ́gẹ́ bí ilé baba wọn:

21. Ti Gáṣónì ni ìdílé Líbínì àti Ṣíméhì; àwọn ni ìdílé Gásónì.

22. Iye àwọn ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọ́n jẹ́ oṣù kan ó lé, jẹ́ ẹgbàata ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ (7,500).

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 3