Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 3:5-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Olúwa sọ fún Mósè pé,

6. “Kó ẹ̀yà Léfì wá, kí o sì fà wọ́n fún Árónì àlùfáà láti máa ràn-án lọ́wọ́.

7. Wọn yóò máa ṣiṣẹ́ fún un àti fún gbogbo ìjọ ènìyàn ní Àgọ́ Ìpàdé bí wọ́n ti ń ṣiṣẹ́ ìsìn nínú àgọ́.

8. Wọn yóò máa tọ́jú gbogbo ohun èlò inú Àgọ́ Ìpàdé, wọn yóò sì máa ṣe ojúṣe àwọn ọmọ Ísírẹ́lì nípa ṣíṣe iṣẹ́ nínú àgọ́.

9. Fi ẹ̀yà Léfì jìn Árónì àti àwọn ọmọ rẹ̀, àwọn nìkan ni a fi fún Árónì nínú gbogbo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.

10. Kí o sì yan Árónì àti àwọn ọmọ rẹ̀ láti máa ṣiṣẹ́ àlùfáà; ẹnikẹ́ni tó bá súnmọ́ ibi mímọ́ pípa ni kí ẹ pa á.”

11. Olúwa tún sọ fún Mósè pé,

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 3