Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 3:15-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. “Ka àwọn ọmọ Léfì nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn kí o ka gbogbo ọmọkùnrin láti ọmọ oṣù kan sókè”

16. Mósè sì kà wọ́n gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa ti pa á láṣẹ fún un.

17. Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Léfì:Gáṣónì, Kóhátì àti Mérárì.

18. Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Gáṣónì:Líbínì àti Ṣíméhì.

19. Àwọn ìdílé Kóhátì ni:Ámírámù, Ísíhárì, Hébírónì àti Yúsíélì.

20. Àwọn ìdílé Mérárì ni:Málì àti Músì.Wọ̀nyí ni ìdílé Léfì gẹ́gẹ́ bí ilé baba wọn:

21. Ti Gáṣónì ni ìdílé Líbínì àti Ṣíméhì; àwọn ni ìdílé Gásónì.

22. Iye àwọn ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọ́n jẹ́ oṣù kan ó lé, jẹ́ ẹgbàata ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ (7,500).

23. Àwọn ìdílé Gáṣónì yóò pa ibùdó sí ìhà ìwọ̀ oòrùn lẹ́yìn àgọ́.

24. Olórí àwọn ìdílé Gáṣónì ni Eliásáfì ọmọ Láélì.

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 3