Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 3:14-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mósè ní ihà Ṣínáì pé,

15. “Ka àwọn ọmọ Léfì nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn kí o ka gbogbo ọmọkùnrin láti ọmọ oṣù kan sókè”

16. Mósè sì kà wọ́n gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa ti pa á láṣẹ fún un.

17. Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Léfì:Gáṣónì, Kóhátì àti Mérárì.

18. Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Gáṣónì:Líbínì àti Ṣíméhì.

19. Àwọn ìdílé Kóhátì ni:Ámírámù, Ísíhárì, Hébírónì àti Yúsíélì.

20. Àwọn ìdílé Mérárì ni:Málì àti Músì.Wọ̀nyí ni ìdílé Léfì gẹ́gẹ́ bí ilé baba wọn:

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 3