Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 3:13-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. nítorí pé ti èmi ni gbogbo àkọ́bí. Ní ọjọ́ tí mo pa gbogbo àkọ́bí ní ilẹ̀ Éjíbítì ni mo ti ya gbogbo àkọ́bí sọ́tọ̀ ní Ísírẹ́lì yálà ti ènìyàn tàbí ti ẹranko. Gbogbo wọn gbọdọ̀ jẹ́ ti èmi. Èmi ni Olúwa.”

14. Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mósè ní ihà Ṣínáì pé,

15. “Ka àwọn ọmọ Léfì nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn kí o ka gbogbo ọmọkùnrin láti ọmọ oṣù kan sókè”

16. Mósè sì kà wọ́n gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa ti pa á láṣẹ fún un.

17. Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Léfì:Gáṣónì, Kóhátì àti Mérárì.

18. Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Gáṣónì:Líbínì àti Ṣíméhì.

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 3