Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 3:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ìwọ̀nyí ni ìdílé Árónì àti Mósè ní ìgbà tí Olúwa bá Mósè sọ̀rọ̀ ní òkè Sínáì.

2. Orúkọ àwọn ọmọ Árónì nìwọ̀nyí, Nádábù ni àkọ́bí, Ábíhù, Élíásárì àti Ítamárì.

3. Orúkọ àwọn ọmọ Árónì nìwọ̀n yìí, àwọn àlùfáà tí a fi òróró yàn, àwọn tí a fi joyè àlùfáà láti siṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí àlùfáà.

4. Ṣùgbọ́n Nádábù àti Ábíhù ti kú níwájú Olúwa nígbà tí wọ́n rú iná àjèjì níwájú Olúwa nínú ijù Sínáì, àwọn méjèèjì kò sì ní ọmọ. Báyìí Élíásárì àti Ítamárì ló sisẹ́ àlùfáà nígbà ayé Árónì baba wọn.

5. Olúwa sọ fún Mósè pé,

6. “Kó ẹ̀yà Léfì wá, kí o sì fà wọ́n fún Árónì àlùfáà láti máa ràn-án lọ́wọ́.

7. Wọn yóò máa ṣiṣẹ́ fún un àti fún gbogbo ìjọ ènìyàn ní Àgọ́ Ìpàdé bí wọ́n ti ń ṣiṣẹ́ ìsìn nínú àgọ́.

8. Wọn yóò máa tọ́jú gbogbo ohun èlò inú Àgọ́ Ìpàdé, wọn yóò sì máa ṣe ojúṣe àwọn ọmọ Ísírẹ́lì nípa ṣíṣe iṣẹ́ nínú àgọ́.

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 3